Adekunle Gold | |
---|---|
Orúkọ àbísọ | Adekunle Kosoko |
Ọjọ́ìbí | 28 Oṣù Kínní 1987 Lagos State |
Irú orin | |
Occupation(s) |
|
Instruments | |
Years active | 2010–present |
Associated acts | |
Website | adekunlegold.com |
Adekunle Almoruf Kosoko (tí a bí ní Oṣù Kìíní Ọjọ́ kejìdínlọ́gbọ̀n, Ọdún 1987), tí a mọ̀ gẹ́gẹ́ bíi Adekunle Gold àti AG Baby, jẹ́ olórin ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, akọrin sílẹ̀ ati ayàwòrán. [1] Ó di ìlúmọ̀ọ́ká olórin lẹ́yìn tí ó kọ orin kan tí a mọ̀ sí “Ṣadé” ní ọdún 2015. Ní ọdún 2015, ó fọwọ́síwèé àdéhùn ìgbàsílẹ̀ pẹ̀lú YBNL Nation tí ó sì gbé orin [[studio]] kan jáde tí àkọ́lé rẹ̀ ń jẹ́ Gold, èyí tí ó wà ní ipò keje ti Billboard àgbáyé. Ṣáájú Gold ni ó ti kọ àwọn orin mẹ́ta kan tí àkọ́lé wọn ń jẹ́ "Sade", "Orente" ati "pick up". Adekunle Gold fi hàn sí Ilé Ìdanilárayá Nàìjíríà lónìí pé ṣáájú kí ó tó f'ọwọ́ sí pẹ̀lú YBNL, ó ṣe àpẹẹrẹ aami ti ilé-iṣẹ́ náà àti pé ó parí àwọn àpẹẹrẹ mìíràn fún Lil Kesh, Viktoh àti Olamide.[2]
Adékúnlé Kòsókó tí a bí sí ìdílé Ọba Kòsókó ní Ìpínlẹ̀ Èkó, Nàìjíríà ní ọjọ́ kejì-dín-lọ́gbọ̀n ọdún 1987.
Ó gboyè HND ní ilé-ẹ̀kọ́ giga ti ìpínlẹ̀ Èkó. [3]
Adekunle gbé Simi níyàwó nínú ayẹyẹ ìsọkan tí wọn kò jẹ́ kí ìlú tàbí àgbáyé mọ̀ sí ní oṣù kìíní ọdún 2019.[4] Ó fi hàn lẹ́hìn náà pé wọ́n ti ní ìbáṣepọ̀ fún ọdún márùn-ún.[5] Wọ́n ṣe ìtẹwọ́gbà ọmọbìnrin tí wọ́n bí ní oṣù kárùn-ún ọdún 2020.[6]
Lákòókò tí ó ń dàgbà, Adékúnlé bẹ̀rẹ̀ sí ní nífẹ̀ẹ́ sí orin nígbà tí ó ń tẹ́tí sí àwọn orin King Sunny Ade àti Ebenezer Obey. Nígbà tí ó wà lọ́dọ̀ọ́, ó dára pọ̀ mọ́ àwọn akọrin ìjọ rẹ̀. Ó sì kọ orin àkọ́kọ́ rẹ̀ nígbà tí ó pé ọmọ ọdún mẹ́ẹ̀dógún. Ní ọdún 2014, Adékúnlé pinnu àti dá dúró lẹ́yìn tí ó yapa kúrò nínú ẹgbẹ́ kan tí ó dara pọ̀ mọ́ nígbà tí ó wà ní ilé-ìwé. Ní ọjọ́ kọkàndínlógún oṣù kejìlá ọdún 2014, ó gbé orin kan jáde tí àkọ́lé rẹ̀ ń jẹ́ "Sade", "one's direction" àti "story of my life" Orin náà tàn ká lè a sì yàn-án bí i orin tí ó dára jù lọ ní ọdún 2015.[7]
Year | Award ceremony | Prize | Recipient/Nominated work | Result |
---|---|---|---|---|
2016 | Nigeria Entertainment Awards | Best Song | Pick Up | Gbàá |
Best New Act to Watch | Himself | Gbàá | ||
2016 | The Headies | Best Alternative Song | "Sade" | Gbàá |
2015 | Nigeria Entertainment Awards | Best New Act | "Himself" | Gbàá |
2017 | City People Entertainment Awards | Album of the Year | "Himself" | Gbàá |
2017 | City People Entertainment Awards | Collabo of the Year | "Himself and Simi" | Gbàá |
2017 | IARA | Best African Music Artist | "Himself" | Gbàá |